ORIN 20
O Fún Wa Ní Ọmọ Rẹ Ọ̀wọ́n
-
1. Nígbà tó dà bíi pé
Kò sírètí fún wa,
Jèhófà fi ẹ̀jẹ̀
Ọmọ rẹ̀ rà wá!
Gbogbo ìgbé ayé
Wa lá ó máa fi sìn ọ́;
A ó sì sọ fáráyé,
Kí ìfẹ́ rẹ lè ṣẹ.
(ÈGBÈ)
Títí ayérayé,
A ó pa ohùn wa pọ̀
Láti máa kọrin ọpẹ́
pó o fún wa lọ́mọ rẹ ọ̀wọ́n.
-
2. Àánú rẹ, inúure,
Ń mú kí a sún mọ́ ọ.
À ń fi orúkọ rẹ
Pè wá, ó wù wá.
Ṣùgbọ́n ẹ̀bùn tó ga,
Tó ṣeyebíye jù
Ni ikú Ọmọ rẹ
Tó jẹ́ ká lè ríyè.
(Ègbè)
Títí ayérayé,
A ó pa ohùn wa pọ̀
Láti máa kọrin ọpẹ́
pó o fún wa lọ́mọ rẹ ọ̀wọ́n.
(ÌLÀ ÀKỌPARÍ)
À ń fàdúrà dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Jèhófà.
O ṣeun tí o fún wa ní Ọmọ rẹ ọ̀wọ́n.
(Tún wo Jòh. 3:16; 15:13.)